Sunday, January 29, 2017

BÀÁLÙ-ÒFURUFÚ TI TINÚBU NI WỌ́N FI KÓ ...




Bàálù òfurufú tí wọ́n fi gbé ọ̀gbẹ́ni Yahyah Jammeh lọ sí orílẹ́-èdè Guinea jẹ́ ti Bọ́lá Tinúbu. Ó gbe é lẹ̀ kí ọ̀gbẹ́ni Jammeh fi kúrò ní Gambia, kí wàhálà má bàá ṣẹlẹ̀ níbẹ̀.

Fún ìgbà mélòó tó kù kí ọ̀gbẹ́ni Jammeh lọ fara sinko sí orílẹ̀-èdè Guinea ni ó ti bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣe owó ìlú kúmọkùmọ, ó tún fi bàálù-òfurufú akẹ́rù kó ọkọ̀ bọ̀gìnì-bọ̀gìnì kúrò ní Gambia. Ìròyìn sọ pé owó tó kó ju mílíọ̀nù mẹ́wàá dọ́là lọ.

Ẹnìkan tó súnmọ́ Aṣìwájú sọ pé bàálù-òfurufú náà ti wà lọ́dọ̀ Aàrẹ tìlú Guinea tipẹ́ nítorí ọ̀rẹ́ ni Tinúbu àti Aàrẹ náà. Bàálú náà gbé ọ̀gbẹ́ni Yahyah Jammeh, ìyàwó ẹ̀, ọmọ ẹ̀ àti ọ̀gbẹ́ni Conde tíí ṣe Aàrẹ orílẹ̀-èdè Guinea kúrò ní Gambia ni ọjọ́ ajé.          #Post-Nigeria

No comments:

Post a Comment