Wednesday, November 29, 2017

WỌN PAṢẸ FUN AWỌN OLOGUN LATI KỌ EDE IGBO, HAUSA ATI YORUBA.

.




Aṣẹ ti wa fun awọn ọmọ-ologun orilẹ-ede Naijiria ki wọn kọ ede igbo, Hausa ati Yoruba ki ọdun 2019 to wọle de.Agbẹnusọ awọn ologun, Usaman Sani lo sọ eyi di mimọ ni ọjọru pe idi ti wọn fi gbe eto yi jade ni pe o ma jẹ ki awọn ọmọ-ologun orilẹ-ede Naijiria le sọ awọn ede mẹta to ṣe pataki lorilẹ ede naa. Atipe ti rogbodiyan ba ṣẹlẹ, ko ni nira fun ologun kan kan lati le ba awọn ara adugbo naa sọrọ.

Wọn sọ siwaju si pe awọn to ba fẹ darapọ mọ awọn ọmọ ologun nisinyin, mimọ ede Hausa, igbo ati Yoruba  ma jẹ anfani pataki. Ko to di igbayi, wọn ti rọ awọn ọmọ ologun orilẹ-ede Naijiria lati mọ ede Faranse, Arabiki ati bẹẹ bẹẹ lọ.

Thursday, November 16, 2017

IRẸMỌLẸKUN







Ọkan lara awọn aṣa ilẹ Yoruba ti igbalode ti gba lọwọ wa ni irẹmọlẹkun (rirẹ ọmọ lẹkun), eyi ni pipẹtu si inu ọmọ to ba n sunkun agaga ọmọ ọwọ. O ṣẹni laaanu pe aṣa yi wa lara awọn aṣa to ti n di igbagbe nitori ọlaju. Ni ode oni, ọpọ iya la ma roju koko ni kete ti ọmọ wọn ba n sunkun, omiran a ma bere lọwọ ọmọ ti ko mọ nkan pe ‘ṣe bi o ṣẹ jẹun tan ni?’, ọpọ a ti ẹ ma bi ọmọ naa ohun to n ṣe bii ki ọmọ da lohun. Ọpọ nnkan ni ọmọ to n sunkun le fẹ; bii ki ebi ma pa, ko fẹ sun ati bẹẹ bẹẹ lọ. 

Irẹmọlẹkun jẹ ọna kan gboogi lati jẹ ki ọmọ dakẹ igbe, ọpọlọpọ igba si ni wọn maa n lo o lati jẹ ki ọmọsun-un. Ọna meji la le gba rẹ ọmọ lẹkun; Oriki ati Orin. Awọn ọna meji yi lo maa n ṣiṣẹ bi idan.

Oriki ni ilẹ Yoruba wulo fun ọpọlọpọ nnkan, lara wọn ni irẹmọlẹkun. Oriki le jẹ ti idile (baba tabi iya) abi orukọ amutẹrunwa ( aina, ojo, ige...). Ti ọmọ ba n sunkun, ti iya ẹ si ran oriki ẹ lẹnu o di dandan ki o dakẹ igbe to ba jẹ olori gaari. Amọ iya melo lo mọ oriki idile ka to wa so oriki orukọ amutọrun wa.

Awọn orin ti a n lo lati rẹmọlẹkun nilẹ Yoruba pọ jantirẹrẹ, awọn orin yi maa n ni anfani lori awọn ọmọ yatọ si ki wọn dakẹ igbe.Ta ba tẹti si awọn orin irẹmọlẹkun daadaa a ma ṣakiyesi pe o kun fun iwure, ko si si ọrọ odi ninu ẹ rara. Apẹẹrẹ ni;

Ta lo naa o                            
Ẹyẹ ni o
Soko ba o,
Ko salọ o.

Jide nkọ o,
O wa nile o
Ki lo n ṣe o
O n kọle lọ wọ
O n ralẹ lọwọ
Ile alaja melo?
Ile alaja mẹta
O kọ ikan fun mama,
O kọ ikan fun baba,
Oun na mu ri ẹ,
Ẹ le jẹ ka mọ orin irẹmọlẹkun tẹ mọ...

BÍ A SÈ LÈ GBÁDÙN ÌGBÉ-AYÉ ÌFẸ̀YÌNTÌ WA.





Bo tilẹ jẹ pe ọpọ oṣiṣẹ ni ko fẹ fẹyinti, ti awọn omiran si n bẹru bi igbe-aye wọn ṣe ma ri ti wọn ba fẹyinti lẹnu iṣẹ. Ba fẹ, ba kọ, ọjọ isinmi a de. Ohun to tọna ka ṣe ni ka gbaradi fun nitori yoruba bọ wọn ni ‘ O n bọ, o n bọ, awọn laa dẹ dee.’ Ti ọjọ-ori o ba fẹyin wa ti, iye ọdun ta lo lẹnu iṣẹ ma fi eyin wa ti. Aitete feyinti awọn to ti dagba wa lara idi ti ko fi si iṣẹ lode oni. Ọpọ to ti fẹyinti lo ni arun igba (stroke) nitori ara wọn ti yi mọ ki wọn maa ṣiṣẹ.

Ọpọlọpọ lo fẹ ba ile-iṣẹ ijọba ṣiṣẹ nitori owo ifẹyinti ti wọn ma gba amọ yatọ si ki owo wa alpo, o ni awọn nkan ti agbọdọ ma ṣe ka ba le gbadun aye-ifẹyinti. Ohun akọkọ fun awọn to ba n ṣiṣẹ aladani ni ki wọn ma da owo-ifẹyinti. Ọpọ ile-iṣẹ lo wa ti o n gba owo ifeyinti.

Ohun miran ti a le ma fi akoko wa ṣe ni ka lọ si agbo ariya tabi apejẹ. Ọpọ eniyan ni ko ni akoko fun awọn mọlẹbi ẹ nigba ti o wa lẹnu iṣẹ. Akoko ifẹyinti jẹ igba ti a le lo pẹlu awọn to sunmọ wa ki ẹlẹmi to de.

Ni akoko ifẹyinti, a ni lati ma fi aye silẹ fun idaraya nitori ilera ara wa ṣe koko. Ka ma sai lọ si ile-iwosan fun ayewo nitori ilera lọrọ. Aikiyesi ilera ara wọn ni ọpọ awọn to ti fẹyinti ṣe ma n ni igba.

Ti owo ba wa, a le da ajọ to n ran awọm alaini lọwọ silẹ tabi ka fi akoko wa fun ohun kan ti a fẹ ki iyipada deba ni ayika tabi agbegbe wa. Eyi ma mu irẹwẹsi kuro ni ara ati pe a jẹ ki ara wa ji pepe.

Ni akotan, aififẹ han ati airi ẹni fẹ wa laraohun to n fa iku aitọjọ. Ka ri pe a ni eeyan lọdọ tabi ka ko lọ si ọdọ awọn mọlẹbi ti wa ni tosi. Mo mọ pe oye eyi ni ọpọ afẹyinti ṣe n lọ si ilu abinibi wọn ni kete ti wọn ba ti gba iwe ifẹyinti wọn.

Wednesday, November 15, 2017

AGBEKALẸ ẸGBẸ ALAGBỌN NI IPINLẸ EKO






Ni anọ ni ipinlẹ Eko ni a ṣe agbekalẹ ẹgbẹ awọn alagbọn. Awọn wọnyi ni ijọba ipinlẹ Eko damọ gẹgẹ bi ẹni to n gbin ati to n sọ agbọn di ohun-elo. Inu agbala ‘Agric Deẹelopment Project’ ni ayẹyẹ naa ti waye ti awọn eeyan jankan-jankan ni eto agbẹ o gbẹyin nibẹ. Lara awọn to wa fun igbekalẹ naa ni; Ọtunba Fẹmi Oke to jẹ alaga ẹgbẹ awọn agbẹ ni ipinlẹ Eko, Hon. Ganiu Sanni to jẹ olubadamọran si gomina ipinlẹ Eko nipa ohun ọgbin, Alhaji Mohammed Mustapha to jẹ alaga fun awọn alagbọn, Arabinrin Tokunbọ, Ọgbẹni Ọlawale Ọnasanya.

Ninu ọrọ iṣide ọgbẹni Ọnasanya, o jẹ ka mọ pe ọdun 2016 ni ijọba ipinlẹ Eko ti pese ilẹ fun awọn to nifẹsi lati gbin agbọn. O ni kii ṣe ilẹ nikan ni ijọba ipinlẹ eko fi ran wọn lọwọ, wọn pese awọn irin-iṣẹ igbalode ti wọn fi le ma sọ agbọn naa di awọn ohun-elo yatọ si pe a fẹ jẹ agbọn lasan. Lẹyin eyi ni alaga awọn agbẹ, Ọtunba fẹmi Oke sọ pe awọn ti n duro de iru anfani yi ọjọ pẹ amọ inu awọn dun nitori isinyi to de naa ko tii pẹ ju. O ni awọn ẹgbẹ agbẹ wa lẹyin wọn bi ike.

 Alhaji Mustapha wa dupẹ lọwọ gbogbo awọn ti wọn wa fi ijoko yẹ wọn si, o ni ẹgbẹ ti wọn gbe kalẹ yi wa fun gbogbo eeyan to nifẹsi ati maa gbin agbọn. Wọn ni eyi pese iṣẹ fun awọn ti ko ni nitori awọn eeyan kan lo n ba awọn ṣe irinṣẹ to n sọ agbọn di ohun-elo.

Alhaji Mustapha wa sọ siwaju awọn nnkan ti a le ri ninu agbọn bi, ororo, a le fi ṣe ọṣẹ, a le fi se ounjẹ, a le fi ṣe burẹdi ati bẹẹ bẹẹ lọ. O rọ awọn eniyan ki wọn darapọ mọ awọn atipe awọn ti wọn ba ni oko agbọn tẹlẹ naa le jẹ anfani eyi nipa gbigbe ohun ere oko wa si ọdọ wọn ni Ẹpẹ lati sọ di ohunkohun to ba wu.


LAKE RICE ṢI N TA WARA WARA.






Lẹyin awuyewuye pe igba ọdun  nikan ni ijọba ipinlẹ Eko ma n ta irẹsi ti wọn fọwọsowọpọ pẹlu ipinlẹ Kebbi ṣe ti a mọ si ‘Lake rice’ ni gomina Akinwunmi mbọde ti ṣe ikede pe awọn irẹsi naa ti wa ni awọn ibi ti wọn ti n ta atipe gbogbo eeyan lo wa fun.
Ninu ikede ti kọmiṣọna fun ọgbin, Ọnọrebu Oluwatoyin Suarau sọ leni fun awọn oniroyin ni Alausa pe ijọba ipinlẹ Eko ti pese ibi ti a ti le ri irẹsi naa ra yatọ si ile ijọba ibilẹ ogun ati LCDA to wa ni ipinlẹ Eko ti a ti n ra a tẹlẹ. Awọn ibi ti a ti le ri ra naa ni; Fish Farm Estate ni Odogunyan ni Ikorodu; Farmers Mart, Surulere; Agric Input Supply Authority (LAISA), Ojo; Agricultural Development Authority (ADA), Oko-ọba, Agege ati Lagos Teleẹision (LTV), Ikeja.

Ọgbẹni Suarau sọ pe ijọba ipinlẹ Eko n ṣiṣẹ takun takun lati ri pe irẹsi naa wa kaakakiri gbogbo ibi ti wọn ti darukọ loorekore atipe iye ti wọn ta irẹsi naa ko tii yi pada nitori ijọba fẹ ki gbogbo eeyan ipinlẹ Eko ri ra ni owo pọku.