Friday, July 28, 2017

NÀÍJÍÍRÍÀ PÀDÁNÙ TÓ MÍLÍỌ̀NÚ MÁRÙNDÍNLÓGÚN SỌ́WỌ́....





Ile aṣoju-ṣofin ti jẹ ka mọ pe orilẹ-ede Naijiiria n padanu to miliọnu marundinlogun sọwọ awọn to n ta nnkan ini orilẹ-ede naa ni ọna aitọ. Awọn nkan ini naa ni wọn ta ku nigbati wọn n sọ ile-iṣẹ to n pese ina di ti aladani, awọn nnkan wonyi ni ko si fun pipese ina. Wọn gbọ pe awọn kan n ta, awọn miran si n ji awọn ohun ini yi ni wọn wa ni ki igbimọ to n ri si rira ati tita ohun ini ijọba ṣewadii nipa ọrọ naa.
Ninu abọ igbimọ ti wọn ṣe ni anọ ni wọn ti sọpe ijọba Naijiria tọju ohun ini wọn yi si akata NELMCO, eyi ti wọn ni ko ta ohun ini naa lati ri owo san gbese ti ile-iṣẹ naa jẹ ki wọn to taa. Eyi ti o nira lati ṣe. Wọn ni iwadii wọn fi han pe ọpọ ninu awọn ini yi ni wọn ta ni owo ti o kaju ilu, omiran ni wọn fun ileeṣẹ to n pese ina. Igbimọ naa jẹ ko di mimọ pe ṣiṣe ohun ini bayi ti pẹ lati aye Niger dam, ECN ati NEPA.
Wọn jẹ ko ye awọn oniroyin pe awọn ajọ to n risi titọju ohun ini orilẹ-ede Naijiiria n fa ẹru naa mọrawọn lọwọ amọ bayi o ti jasi ọwọ NELMCO wọn si n duro lati gba aṣẹ lọwọ NCP ki wọn to bẹrẹ si ni ta awọn ẹru naa. Ipade lori abọ ohun ini naa ma tẹsiwaju leni lati gbọ ọrọ lẹnu gbogbo ajọ ti ọrọ kan.

No comments:

Post a Comment