Friday, February 3, 2017

ÌDÍ TÍ ÌWÀ ÌBÀJẸ́ ṢE Ń GBÒRÒ SI - Ọ̀GÁ ỌlỌ́PÀÁ.





Olórí àwọn ọlọ́pàá ní orílẹ̀-èdè Nàìríjíà, Ibrahim Idris ti sọ pé lọ́dún tó kọjá nínú bílíọ̀nù mẹ́rìndínlógún náírà tó wà nínú ìsúná-owó fún àwọn ọlọ́pàá, bílíọ̀nù mẹ́rin péré ni ó tẹ àwọn lọ́wọ́.

Ó sọ èyí nínú ìpàdé tí wọ́n ṣe pẹ̀lú ìgbìmọ̀ ilé-aṣòfin tó ń rí sí ọ̀rọ̀ ọlọ́pàá. Ibrahim Idris sọ pé owó tí kò tó, tí wọ́n tún ń yọ nínú ẹ̀ yí ni ó fa ìfàsẹ́yìn fún àwọn ọlọ́pàá láti ṣe iṣẹ́.

Ó sọ síwájú si pé bákan náà ni ọdún 2015, àwọn gba bílíọ̀nù mẹ́jọ ó lé díẹ̀ nínú.

No comments:

Post a Comment