Showing posts with label ede yoruba. Show all posts
Showing posts with label ede yoruba. Show all posts

Monday, January 30, 2017

ÀWỌN OLÓGUN KAN NA ÒJÍṢẸ́ ỌLỌ́RUN DÁKÚ NÍTORÍ...




Òjíṣẹ́ Ọlọ́run ti ìjọ Ìràpadà t’Ọlọ́run (RCCG), Alex Ochienu ló sọ bí ológun méjì ṣe na òun títí t’óùn fi dákú nítorí wọ́n ní kí òun fa etí, kí óun sì ma kúrú-ga. Éyí tí òun kọ láti ṣe.

Gẹ́gẹ́ bí ohun tí òjíṣẹ́ Ọlọ́run náà sọ, Cpl. M. Dankwa ló kọ́kọ́ nàá kí ológun kejì tí kò mọ orúkọ ẹ̀ to fọwọ́ kun. Ó sọ síwájú si pé wọ́n na òun tí òun sì dákú. Ọpẹ́lọpẹ́ àwọn tó wà nítòsí ló gbé òun lọ sí ilé-ìwòsàn tìjọba tó wà ní Gwarimpa ni Abuja.

Thursday, January 26, 2017

AJÁ TÓKẸ́ MÁKINWÁ JẸ BÀTÀ IYEBÍYE.




Sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ orí rédíò, Tókẹ́ Mákinwá ni ajá ẹ̀ tó ti pé oṣùn mẹ́jọ jẹ bàtà olówó iyebíye ẹ̀. 


Inú bí Tókẹ́ nítorí owó bàtà náà ju ọ̀ọ̀dúnrún náírà lọ. Èyí ló mu tó fi gbé ‘fọ̀ sẹẹ̀lì’ lé ajá nà lórí snapchat.
 
Ọ̀rọ̀ yí dàbí ẹran Ọba tó mú iṣu Ọba jẹ... kí Tókẹ́ sọọ́ di isó inú ẹ̀kú, àmú mọ́ra.

Thursday, January 19, 2017

Ẹ KÁÁBỌ̀ SÍ ...


Èyí ni láti kí i yín káàbọ̀ sí ‘Yorùbá Online News’, ibi tí ẹ̀ ti ma gbádùn kíka ìròyìn lédè Yorùbá. A ti pinu láti ma mú ìròyìn wa fún kíkà yín, ìròyìn nípa ètò-òṣèlú, eré-ìdárayá, òwò, àwon olórin àti òṣèré, àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ.

A ri pé ó tó àkókò láti gbé èdè Yorùbá ga nípasè ìròyìn ṣíṣe. A mọ̀ pé ọ̀pọ̀ ló ti bẹ̀rẹ̀ irúfẹ́ ohun báyìí àmọ́ wọn ò ní àǹfàní láti tẹ̀síwájú nítorí ìdí kan tàbí òmírán. Àwá kán lùú nítorí ìfẹ́ ta ní sí èdè Yorùbá àti ìfẹ́ jíjẹ́ kí àwọn èyàn mọ ohun tó ń lọ ní àyíká wọn.
Gbogbo ohun tó jẹ́ kí àwọn aṣájú má lè tẹ̀síwájú lati fi sọ́kàn, èyí ló jẹ́ ka pinu pé:
1.     Gbogbo ohun tí àwọn elédè Gẹ̀ẹ́sì bá kọ lórí ìròyìn kan ni a ma pòpọ̀ ta ma kọ fún kíkà yin-ín lédè Yorùbá. Èyí ni láti dín iṣẹ́ ògbúfọ ṣíṣe kù àti láti jẹ́ kẹ mọ òye òótọ́ ìròyìn náà.

2.     Èdè Yorùbá àjùmọ̀lò ni a ma fi kọ ìròyìn, ẹ foríjì wá tí èdè àyálò bá pọ̀jù.
3.     Bí ìròyìn náà ṣe ń jáde lédè Gẹ̀ẹ́sì, a ma sa ipa àti agbára wa láti ri pé ìròyìn náà kò pẹ́ kàn yín lára.

4.     A ma nílò èrò yin nítorí igi kan kò lè dágbó ṣe, àjèjì ọwọ́ kan ò gbẹ́rù dórí.
Ka tó bẹ́ lu agbami ìròyìn, a ma sọ nípa èdè Yorùbá àti òǹkà Yorùbá.
Ẹ sẹ́ tí ẹ darapọ̀ mọ́ wa, ẹ m báwa ká lọ. Àjọṣepọ̀ o nì bàjẹ́ (Áṣẹ). Ẹ ò ní wá wa tì (Áṣẹ)

Ẹ MA BÁWA KÁ LỌ!!!