Tuesday, October 10, 2017

OOTỌ NIPA OWO IRANWỌ TI CBN FUN AWỌN AGBẸ IPINLẸ EKO.






Lati ro awọn agbẹ lagbara lati le ‘roko bọ́dún dé’, ile-ifowopamọ tilẹ Naijiria (CBN) gbe eto ẹyawo kalẹ funn gbogbo agbẹ to wa lorilẹ-ede Naijiria eyi ti gbogbo awọn agbẹ ti n jẹ mudun mudun ẹ afi awọn agbẹ to wa ni ipinlẹ ilu Eko.
Ninu ipade awọn ẹgbẹ agbẹ ti ipinlẹ Eko eyi ti akọroyin wa Bajepade Abayomi wa nibẹ ni a gbọ pe awọn agbẹ ipinlẹ Eko letọ si owo iranwọ to to biliọnu meji naira. Alaga ẹgbẹ naa Ọtunba fẹmi Oke jẹ ka mọ pe ninu biliọnu meji naira yi, biliọn kan naira ni ẹgbẹ naa le gba atipe ti wọn ba fẹ gba biliọnu naa wọn nilo ohun ti wọn ma fi duro. Nigbati wọn ṣe iwadii, wọn ri pe ni awọn ipinlẹ bii Ogun, Oṣun, Kwara ati Ọyọ ti wọn ti ri owo tiwọn gba ijọba ipinlẹ naa lo bawọn gba owo naa. Wọn ka si ijọb pinlẹ Eko lati ri pe ẹgbẹ agbẹ pinlẹ Eko ri owo tiwọn gba amọ nnkan ko ti ṣẹnure fun wọn.
Ninu ifọrọwerọ ti wọn ni pẹlu ijọba ipinlẹ Eko, ijọba sọ pe bi owo naa ṣe ma di dida dapada gan lo jẹ awọn logun nitori awọn ko le rọ owo ti awọn o ya lo san pada. Ohun ti ẹgbẹ naa pinu si ni pe awọn ma lo ẹgbẹ alajẹṣẹku to wa ninu ẹgbẹ naa atipe bi ijọba ba funkun mọ ẹgbẹ, ẹgbẹ ma fi tipa tipa mu awọn olori alajẹṣẹku naa eyit i owo naa asi di gbigba pada.
Igba-keji alaga to sọrọ rọ awọn ọmọ ẹgbẹ ki wọn maa dẹkun adura ki ijọba le gba atipe ki ijọba naa ma wo awọn niran nitori ti owo naa o ba di gbigba yoo kan wa ni bẹ ni. Atipe ti wọn ba le ri gba, awọn agbẹ ma le ri owo ṣagbẹ. Ipe wa lọ si ọdọ ijọba pe ti wọn ba le ri owo naa gba, wọn le fi ọwọ sowọpọ pẹlu awọn agbẹ to jẹ pe wọn ma ra awọn ere oko naa ti wọn si le fojuto bi owo naa ṣe n di dida pada.